“Abala igbagbọ”

“Idahun- Allahu ni Oluwa mi ẹni ti o ṣe pe Oun ni O n tọju mi ti O si n tọju gbogbo agbaye pẹlu idẹra Rẹ.
“Ẹri ni:
Ọ̀rọ̀ Rẹ -Ọba ti ọla Rẹ ga-: “ Gbogbo ọpẹ́ ń jẹ́ ti Allāhu, Olúwa gbogbo ẹ̀dá, 2 [Surah Al-Fâtihah: 2]

"Idahun- Ẹsin mi ni Isilaamu, oun ni: Jijupa-jusẹ fun Ọlọhun pẹlu igbagbọ ninu Ẹ ni Oun nikan ṣoṣo, ati itẹriba fun Un pẹlu itẹle, ati mimọ kuro nibi ẹbọ ati awọn ẹlẹbọ. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
Dájúdájú ẹ̀sìn t’ó wà lọ́dọ̀ Allāhu ni ’Islām. [Surah Âl-`Imrân: 19]"

"Idahun- Anọbi Muhammad (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a). "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
{Muhammad ni Òjíṣẹ́ Allāhu ...} "[Surah Al-Fath: 29]"

"Idahun- Kalmatut Taohīd ni "Laa ilaaha illallahu", itumọ ẹ ni pe: Ko si ẹni tí ijọsin ododo tọ si afi Allahu. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
Nítorí náà, mọ̀ pé dájúdájú kò sí ọlọ́hun tí ìjọ́sìn tọ́ sí àfi Allāhu. "[Suuratu Muhammad: 19]"

"Idahun- Ọlọhun n bẹ ni sanmọ lori itẹ-ọla, lori gbogbo ẹda, Ọba -ti ọla Rẹ ga- sọ pe: " "{Àjọkẹ́-ayé gúnwà sórí Ìtẹ́-ọlá 5} "[Surah Tâ-hâ: 5]" O sọ pe: "{Òun sì ni Olùborí t’Ó wà lókè àwọn ẹrú Rẹ̀. Òun ni Ọlọ́gbọ́n, Onímọ̀-ìkọ̀kọ̀ 18} "[Surah Al-An`âm: 18]"

"Idahun- Itumọ ẹ ni pe: Ọlọhun ni O ran an si gbogbo aye ni olufunni ni iro ìdùnnú ati olukilọ "
"O si jẹ dandan: "
"Titẹle e nibi nnkan to ba pa laṣẹ. "
"Gbigba a lododo nibi nnkan ti o ba sọ. "
"Ki a ma ṣẹ ẹ. "
"Ki a ma jọsin fun Ọlọhun afi pẹlu nnkan ti O ṣe lofin, oun ni itẹle oju-ọna ojiṣẹ Ọlọhun ati gbigbe adadaalẹ ju silẹ. "
"Ọba -ti ọla Rẹ ga- sọ pe-: {Ẹnikẹ́ni t’ó bá tẹ̀lé Òjíṣẹ́ náà, ó ti tẹ̀lé (àṣẹ) Allāhu...} [Suuratun Nisâ': 80], O tun sọ- mimọ ni fun Un- pe: {Àti pé kò níí sọ̀rọ̀ ìfẹ́-inú 3 Kò níí sọ ohun kan tayọ ìmísí tí A fi ránṣẹ́ sí i 4} "[Suuratun Najm: 3, 4] "Ọba - ti O lágbára ti O gbọnngbọn - sọ pe: " "{Dájúdájú àwòkọ́ṣe rere wà fun yín lára Òjíṣẹ́ Allāhu fún ẹnikẹ́ni tí ó bá ń retí (ẹ̀san) Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, tí ó sì rántí Allāhu ní ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ (ìgbà) 21} [Surah Al-Ahzâb: 21]"

"Idahun- O da wa fun ijọsin Rẹ ni Oun nikan ṣoṣo ti ko si orogun kankan fun Un. "
"Ko kii ṣe tori iranu ati ere. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Àti pé Èmi kò ṣẹ̀dá àlùjànnú àti ènìyàn bí kò ṣe pé kí wọ́n lè jọ́sìn fún Mi 56} "[Surah Adh-Dhâriyât: 56]"

"Idahun- Oun ni orukọ kan to ko gbogbo nnkan ti Ọlọhun nífẹ̀ẹ́ rẹ ati nnkan ti O yọnu si ninu awọn ọrọ ati iṣẹ ti o pamọ ati èyí tí o han sinu."
"Eyi to han:
Gẹgẹ bii iranti Ọlọhun pẹlu ahọn ninu iṣe afọmọ, ati idupẹ, ati igbe Ọlọhun tobi, ati kiki irun ati ṣiṣe Hajj. "
"Eyi to pamọ:
Gẹgẹ bii igbarale Ọlọhun ati ibẹru ati agbiyele. "

Idahun- "Nnkan to tobi julọ ti o jẹ dandan fun wa ni: Nini igbagbọ ninu Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- ni Òun nikan ṣoṣo. "

"Idahun-1- Taohīdur Rubūbiyyah: Oun ni nini igbagbọ pe dajudaju Ọlọhun ni Adẹdaa, Olupese, Olukapa, Oluṣeto, ni Oun nikan ṣoṣo ti ko si orogun kankan fun Un. "
"2- Taohīdul 'Ulūhiyyah: Oun ni imu Ọlọhun ni ọkan ṣoṣo pẹlu ijọsin, ti a o si nii jọsin fun ẹnikankan afi Allahu -ti ọla Rẹ ga- "
"3- Taohīdul ’Asmā’i was Sifāt: Oun ni nini igbagbọ ninu awọn orukọ ati awọn iroyin ti Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- ti o wa ninu iwe Ọlọhun ati ọrọ ojiṣẹ Ọlọhun, laisi isafiwe tabi afijọ tabi sisọ pe ko ri bẹẹ. "
"Ẹri awọn iran nini igbagbọ ninu Ọlọhun nikan ṣoṣo mẹtẹẹta ni:
ọrọ Ọba ti ọla Rẹ ga - to sọ pe:" {Olúwa àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ àti ohun tí ń bẹ láààrin àwọn méjèèjì. Nítorí náà, jọ́sìn fún Un, kí ó sì ṣe sùúrù lórí ìjọ́sìn Rẹ̀. Ǹjẹ́ o mọ ẹni tí ó tún ń jẹ́ orúkọ Rẹ̀? 65} " [Surah Maryam: 65]"

"Idahun- mimu orogun pẹlu Ọlọhun ti ọla Rẹ ga”
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Dájúdájú Allāhu kò níí foríjin (ẹni tí) ó bá ń ṣẹbọ sí I. Ó sì máa ṣàforíjìn fún ohun mìíràn yàtọ̀ sí ìyẹn fún ẹni tí Ó bá fẹ́. Ẹni tí ó bá ń ṣẹbọ sí Allāhu, dájúdájú ó ti dá àdápa irọ́ (tí ó jẹ́) ẹ̀ṣẹ̀ ńlá 48}" "[Surah An-Nisâ': 48]"

"Idahun- Ash-Shirku: Oun ni gbigbe eyikeyi iran ninu awọn iran ijọsin fun ẹlomiran yatọ si Ọlọhun ti ọla Rẹ ga”
"Awọn iran ẹ: "
"Ẹbọ nla; gẹgẹ bii: Pipe ẹni ti o yatọ si Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga-, tabi fifi ori balẹ fun ẹni ti o yatọ si I -mimọ fun Un-, abi didu ẹran fun ẹni ti o yatọ si Ọlọhun - ti O lágbára ti O si tun gbọnngbọn-. "
"Ẹbọ kekere; gẹgẹ bii:
Bibura pẹlu nǹkan ti o yatọ si Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga-, tabi At-Tamā’im (asokọrun), oun naa ni nnkan ti wọn maa n so kọ lati fi fa anfaani wa tabi ti aburu danu, ati eyi to kere ninu ṣekarimi, gẹgẹ bii ki o maa ki irun rẹ dáadáa latari pe o n ri awọn ti wọn n wo o. "

"Idahun- ẹnikankan o ni imọ ikọkọ afi Ọlọhun nikan ṣoṣo. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Sọ pé: “Àwọn t’ó wà nínú àwọn sánmọ̀ àti ilẹ̀ kò nímọ̀ ìkọ̀kọ̀ àfi Allāhu. Àti pé wọn kò sì mọ àsìkò wo ni A máa gbé àwọn òkú dìde 65} " "[Suuratun Naml: 65]"

"Idahun- 1- Nini igbagbọ ninu Ọlọhun ti ọla Rẹ ga”
"2- Ati awọn Malaika Rẹ."
"3- Ati awọn iwe Rẹ. "
"4- Ati awọn Ojiṣẹ Rẹ."
"5- Ati ọjọ ikẹyin. "
"Ati kadara eyi ti o daa nibẹ ati eyi ti o buru."
"Ẹri ni:
Hadisi Jibril ti o gbajumọ lọdọ Muslim, Jibril sọ fun Anọbi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- pe: " "«Fun mi ni iro nipa igbagbọ, o sọ pe: Ki o ni igbagbọ ninu Ọlọhun, ati awọn Malaika Rẹ, ati awọn iwe Rẹ, ati awọn Ojiṣẹ Rẹ, ati ọjọ ikẹyin, ki o ni igbagbọ ninu kadara eyi ti o daa nibẹ ati eyi ti o buru». "

"Idahun- Nini igbagbọ ninu Ọlọhun ti ọla Rẹ ga: "
"Ki o ni igbagbọ pe dajudaju Allahu ni O da ọ ti O si n pese fun ọ, Oun nikan ṣoṣo ni Olukapa ati Oluṣeto gbogbo ẹda. "
"Oun ni Ẹni ti a n jọsin fun, ko si ẹni ti ijọsin ododo tọ si yatọ si I."
"Dajudaju Oun ni Ọba ti O tobi, Ọba nla, Ọba ti O pe julọ ti O ṣe pe gbogbo ọpẹ patapata n jẹ tiRẹ, awọn orukọ to rẹwa ati awọn iroyin to ga n jẹ tiRẹ, ko si orogun fun Un, nnkankan o si jọ Ọ (mimọ ni fun Un). "
" Nini igbagbọ ninu awọn Malaika:
"
"Awọn ni ẹda ti Ọlọhun da wọn latara imọle, ati fun ijọsin Rẹ ati fun itẹle to pe fun aṣẹ Rẹ"
"Ninu wọn ni Jibrīl -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- wa, ẹni ti o ṣe pe o maa n sọkalẹ pẹlu imisi fun awọn Anọbi."
"Nini igbagbọ ninu awọn iwe:
"
Awọn ni awọn iwe ti Ọlọhun sọ wọn kalẹ fun awọn Ojiṣẹ Rẹ. "
"Gẹgẹ bii Kuraani:
Ti a sọkalẹ fun Muhammad -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-"
"Injīl:
Ti a sọkalẹ fun Isa -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a-"
"Taorah:
Ti a sọkalẹ fun Musa -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a-"
"Zabūr:
Ti a sọkalẹ fun Dāud -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- "
Awọn takada Ibrāhīm ati Mūsa:
Ti a sọkalẹ fun Ibrohim ati Musa."
Nini igbagbọ si awọn ojiṣẹ [Ọlọhun]
"Awọn ni ẹni ti Ọlọhun ran wọn si awọn ẹru Rẹ lati kọ wọn (ni ẹsin), ati lati fun wọn ni iro idunnu pẹlu daadaa ati alujanna, ati lati ṣe ikilọ fun wọn kuro nibi aburu ati ina. "
"Awọn ti wọn lọla julọ ninu wọn ni:
Awọn onipinnu, awọn si ni:
" Nūh -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- "
" Ibrāhīm -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- "
Mūsa -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a-"
"Ēsa -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- "
Muhammad -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-."
Nini igbagbọ si ọjọ ikẹyin.
"Oun ni nnkan to wa lẹyin iku ninu sàréè, ati ni ọjọ ajinde, ati ọjọ igbende ati iṣiro, ni ibi ti awọn ero alujanna o ti maa wa ni awọn ibugbe wọn ti awọn ero ina naa o si maa wa ninu awọn ibugbe wọn."
"Nini igbagbọ ninu kadara eyi to daa ninu ẹ ati eyi to buru:
"
"Al-Qadar (Kadara): Oun ni nini adisọkan pe dajudaju Ọlọhun ni imọ nipa gbogbo nnkan ti o n ṣẹlẹ ninu aye, ati pe O ti kọ yẹn sinu Laohul Mahfūdh (ọpọn ti A n ṣọ ti akọsilẹ gbogbo nkan wa ninu rẹ), O si tun fẹ bibẹ rẹ ati dida a. "
"Ọba ti ọla Rẹ ga- sọ pe {Dájúdájú A ṣẹ̀dá gbogbo n̄ǹkan pẹ̀lú kádàrá 49}[Surah Al-Qamar: 49]."
" Ipele mẹrin ni o ni:
"
"Alakọkọ: Imọ Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga-, ninu iyẹn ni imọ Rẹ to ti ṣaaju gbogbo nnkan, ṣíwájú ṣiṣẹlẹ awọn nnkan ati lẹyin ṣiṣẹlẹ rẹ. "
"Ẹri ẹ ni:
Ọrọ Ọba ti ọla Rẹ ga-: " Dájúdájú Allāhu, ọ̀dọ̀ Rẹ̀ ni ìmọ̀ Àkókò náà wà. Ó ń sọ òjò kalẹ̀. Ó mọ ohun t’ó wà nínú àpòlùkẹ́. Ẹ̀mí kan kò sì mọ ohun tí ó máa ṣe níṣẹ́ ní ọ̀la. Ẹ̀mí kan kò sì mọ ilẹ̀ wo l’ó máa kú sí. Dájúdájú Allāhu ni Onímọ̀, Alámọ̀tán. 34 [Suuratu Luqman: 34].
"Ẹlẹẹkeji:
Dajudaju Ọlọhun ti kọ yẹn sinu Laohul Mahfūdh (ọpọn ti A n ṣọ ti akọsilẹ gbogbo nkan wa ninu rẹ), ati pe gbogbo nnkan to sẹlẹ ati èyí tí yoo ṣẹlẹ jẹ nnkan ti wọn ti kọ si ọdọ Rẹ sinu iwe "
"Ẹri ẹ ni:
Ọrọ Ọba ti ọla Rẹ ga-: " Ọ̀dọ̀ Rẹ̀ sì ni àwọn kọ́kọ́rọ́ ìkọ̀kọ̀ wà. Kò sí ẹni t’ó nímọ̀ rẹ̀ àfi Òun. Ó nímọ̀ ohun tí ń bẹ nínú ilẹ̀ àti odò. Ewé kan kò sì níí já bọ́ àfi kí Ó nímọ̀ rẹ̀. Kò sì sí kóró èso kan nínú òkùnkùn (inú) ilẹ̀, kò sí ohun tútù tàbí gbígbẹ kan àfi kí ó wà nínú àkọsílẹ̀ t’ó yanjú. 59 [Suuratul-An’am: 59].
"Ẹlẹẹkẹta:
Oun ni pe gbogbo nnkan n ṣẹlẹ pẹlu ifẹ Ọlọhun, nnkankan o nii ṣẹlẹ lati ọdọ Rẹ tabi lati ọdọ ẹda Rẹ afi pẹlu ifẹ Rẹ -Ọba ti ọla Rẹ ga- "
"Ẹri ẹ ni:
Ọrọ Ọba ti ọla Rẹ ga-: " "{(Ó wà) fún ẹni tí ó bá fẹ́ nínú yín láti dúró déédé 28 Ẹ̀yin kò sì níí fẹ́ (láti dúró déédé) àyàfi tí Allāhu bá fẹ́, Olúwa gbogbo ẹ̀dá 29} "[Suuratut Takwîr: 28]"
"Ẹlẹẹkẹrin: Nini igbagbọ pe gbogbo nnkan ti o n bẹ ẹda ni wọn ti Ọlọhun da wọn, ti O si da awọn paapaa wọn ati awọn iroyin wọn ati lilọ bibọ wọn, ati gbogbo nnkan ti o n bẹ ninu wọn. "
"Ẹri ẹ ni:
Ọrọ Ọba ti ọla Rẹ ga-: " "{Allāhu l’Ó sì dá ẹ̀yin àti n̄ǹkan tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́ 96} [Surah As-Sâffât: 96]

"Idahun- Ọrọ Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- ni, kii ṣe nnkan ti a da. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
{Tí ẹnì kan nínú àwọn ọ̀sẹbọ bá wá ètò ààbò wá sọ́dọ̀ rẹ, ṣ’ètò ààbò fún un títí ó fi máa gbọ́ ọ̀rọ̀ Allāhu...} [Suuratu At-Tawbah: 6].

Idahun- Oun ni gbogbo ọrọ tabi iṣe tabi ifirinlẹ tabi iroyin ti dida tabi ti iwa ti n bẹ fun Anabi (ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a).

Idahun- Gbogbo nkan ti awọn eeyan ba daalẹ sinu ẹsin, ti ko si si nigba aye Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ati awọn saabe rẹ.
A o nii gba a, ati pe a maa da a pada ni.
Fun ọrọ Anabi - ki ikẹ ati ọla maa ba a - pe: Gbogbo adadaalẹ pata anu ni Abu Daud ni o gba a wa.
Apejuwe rẹ:
Alekun nibi ijọsin, gẹ́gẹ́ bíi ṣiṣe alekun fifọ ẹlẹẹkẹrin nibi aluwala, ati ṣiṣe ayẹyẹ ọjọ-ibi Anabi, ko wa lati ọdọ Anabi - ki ikẹ ati ọla Ọlọhun maa ba a - ati awọn saabe rẹ.

Idahun- Al-Walā’u: Oun ni nini ifẹ awọn onigbagbọ ododo ati ṣiṣe iranwọ fun wọn.
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
{Àwọn onígbàgbọ́ òdodo lọ́kùnrin àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo lóbìnrin, apá kan wọn lọ̀rẹ́ apá kan...}. [Suuratu At-Tawbah: 71].
Al-Barāhu: Oun ni ikorira awọn alaigbagbọ ati iba wọn ṣọta.
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
Dájúdájú àwòkọ́ṣe rere ti wà fun yín ní ara (Ànábì) ’Ibrọ̄hīm àti àwọn t’ó wà pẹ̀lú rẹ̀. Nígbà tí wọ́n sọ fún ìjọ wọn pé: "Dájúdájú àwa yọwọ́-yọsẹ̀ kúrò nínú ọ̀rọ̀ yín àti ohun tí ẹ̀ ń jọ́sìn fún lẹ́yìn Allāhu. A takò yín. Ọ̀tá àti ìkórira sì ti hàn láààrin wa títí láéláé àyàfi ìgbà tí ẹ bá tó gbàgbọ́ nínú Allāhu nìkan ṣoṣo. [Suuratul-Mumtahina: 4].

Idahun- Ọlọhun o nii gba nkan ti o yatọ si Isilaamu.
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
{Ẹnikẹ́ni tí ó bá wá ẹ̀sìn kan ṣe yàtọ̀ sí ’Islām, A ò níí gbà á lọ́wọ́ rẹ̀. Ní Ọjọ́ Ìkẹ́yìn, ó sì máa wà nínú àwọn ẹni òfò 85}. [Suuratu Al-Imran 85]"

"Idahun- Àpẹrẹ ọrọ: Bibu Ọlọhun -mimọ ni fun Un- tabi Ojiṣẹ Rẹ -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-."
"Àpẹrẹ iṣẹ:
Yiyẹpẹrẹ Kuraani tabi fifi ori kanlẹ fun ẹni ti o yatọ si Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- "
"Àpẹrẹ adisọkan:
Didi adisọkan pe nnkankan n bẹ ti o lẹ́tọ̀ọ́ si ijọsin yatọ si Allahu -ti ọla Rẹ ga- tabi pe adẹda kan nbẹ pẹlu Allahu -ti ọla Rẹ ga-. "

"Idahun- "
"1- Sọbẹ-ṣelu nla: Oun ni fifi aigbagbọ pamọ ati ifi igbagbọ han. "
"Yio maa mu ni kuro ninu Isilaamu, o wa ninu aigbagbọ nla. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Dájúdájú àwọn ṣọ̀be-ṣèlu mùsùlùmí yóò wà nínú àjà ìsàlẹ̀ pátápátá nínú Iná. O ò sì níí rí alárànṣe kan fún wọn 145} "[Suuratun Nisaa: 145]"
"2- Sọbẹ-ṣelu (Oju eji) kekere: "
"Gẹgẹ bii: Irọ ati iyapa adehun ati ijanba afọkantan. "
"Ko nii mu ni kuro ninu Isilaamu, o wa ninu awọn ẹṣẹ ati pe ẹni ti o n ṣe e maa lẹ́tọ̀ọ́ si iya. "
"Ojiṣẹ Ọlọhun -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe: " Àmì ti a fi n da munafiki mọ mẹta ni: Ti o ba sọrọ yóò parọ, ti o ba ṣe àdéhùn yóò yapa, ti wọn ba gbára le e yóò jamba "Bukhari ati Muslim ni wọn gba a wa. "

"Idahun- oun ni Muhammad (ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a). "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{(Ànábì) Muhammad kì í ṣe bàbá ẹnì kan kan nínú àwọn ọkùnrin yín, ṣùgbọ́n (ó jẹ́) Òjíṣẹ́ Allāhu àti òpin àwọn Ànábì...} " [Suuratul-Ahzaab: 40]. "- Ojiṣẹ Ọlọhun -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- sọ pe: " «Emi ni opin awọn Anabi, ko si Anabi kankan lẹyin mi» " "Abu Daud ati Tirmidhi ati ẹni ti o yatọ si wọn ni wọ́n gba a wa. "

"Idahun- iṣẹ-iyanu ni: Gbogbo nnkan ti Ọlọhun fun awọn Anabi Rẹ ninu awọn nǹkan eemọ lati da lori ododo wọn, gẹgẹ bii: "
"Lila oṣupa si meji fun Anabi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-. "
"- Pinpin odo si meji fun Musa -ki ikẹ Ọlọhun maa ba a- ati titẹri Fir'aun ati awọn ọmọ ogun rẹ. "

"Idahun- Sàábé ni: Ẹni ti o ba pade Anabi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ti o gba a gbọ ti o si ku sori Isilaamu. "
"- A maa nífẹ̀ẹ́ wọn, a si maa kọ iṣe wọn, awọn ni ẹni ti o dara julọ ti wọn si lọla julọ ninu awọn eeyan lẹyin awọn Anabi. "
"Awọn ti wọn lọla julọ ninu wọn ni awọn arole mẹrẹẹrin:
"
"Abu Bakr -ki Ọlọhun yọnu si i-."
"Umar -ki Ọlọhun yọnu si i-.
"Uthman -ki Ọlọhun yọnu si i-.
"Aliy- ki Ọlọhun yọnu si i-. "

"Idahun- awọn ni awọn iyawo Anabi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Ànábì ní ẹ̀tọ́ sí àwọn onígbàgbọ́ òdodo ju ẹ̀mí ara wọn lọ (nípa ìfẹ́ rẹ̀ àti ìdájọ́ rẹ̀). Àwọn aya rẹ̀ sì ni ìyá wọn} [Suuratul-Ahzaab: 6].

"Idahun- A maa nífẹ̀ẹ́ wọn, a si maavmu wọn ni ọrẹ, a si maa korira ẹni ti o ba korira wọn, a o si nii kọja aala nipa wọn, awọn ni awọn iyawo rẹ ati awọn arọmọdọmọ rẹ, ati awọn ọmọ Hashim ati awọn ọmọ Mutollib ninu awọn onigbagbọ. "

"Idahun- Ojuṣe wa ni: Ṣíṣe apọnle wọn, ati gbigbọ ati titẹle wọn nibi nnkan to yatọ si yiyapa Ọlọhun, ki a si ma jáde le wọn lori, ki a si maa ṣe adura ati iṣiti fun wọn ni kọrọ."

"Idahun- alujanna (ọgba idẹra)" "{Dájúdájú Allāhu yóò mú àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo, tí wọ́n sì ṣe àwọn iṣẹ́ rere wọ inú Ọgbà Ìdẹ̀ra tí àwọn odò ń ṣàn ní ìsàlẹ̀ rẹ̀...} [Suuratu Muhammad: 12].

Ina ni, Ọlọhun ti O ga sọ pe: nítorí náà ẹ ṣọ́ra fún Iná, èyí tí ìkoná rẹ̀ jẹ́ àwọn ènìyàn àti òkúta tí Wọ́n pa lésè sílẹ̀ de àwọn aláìgbàgbọ́. 24 [Suuratul-Baqarah: 24].

Ibẹru: Oun ni bibẹru Ọlọhun ati iya Rẹ.
Ṣíṣe agbiyele:
Oun ni ṣiṣe agbiyele ẹsan lọdọ Ọlọhun ati aforijin Rẹ ati ikẹ Rẹ.
Ẹri:
Ọ̀rọ̀ Ọlọhun Ọba ti O ga: Àwọn wọ̀nyẹn tí wọ́n ń pè (lẹ́yìn Rẹ̀) ń wá àtẹ̀gùn sọ́dọ̀ Olúwa wọn ni! - Èwo nínú wọn l’ó súnmọ́ (Allāhu) jùlọ (báyìí)? – Àwọn náà ń retí ìkẹ́ Allāhu, wọ́n sì ń páyà ìyà Rẹ̀. Dájúdájú ìyà Olúwa rẹ jẹ́ ohun tí wọ́n gbọ́dọ̀ ṣọ́ra fún. 57 [Suuratul-Israa: 57]. Allah tun sọ pe: Fún àwọn ẹrúsìn Mi ní ìró pé dájúdájú Èmi ni Aláforíjìn, Àṣàkẹ́-ọ̀run. 49 Àti pé dájúdájú ìyà Mi ni ìyà ẹlẹ́ta-eléro 50 [Suuratul-Hijr: 49, 50].

Idahun- Ọlọhun, Ọba Olutọju, Onikẹẹ, Olugbọ, Oluriran, Onimimọ, Olupese, Alaaye, Ọba ti O tobi.... ati bẹẹ bẹẹ lọ ninu awọn orukọ ti o dara ati awọn iroyin ti o ga.

Idahun- ALLAAHU: Ìtumọ̀ rẹ ni pe Ọba ti a n sin ni ododo, Oun nikan ni O da wa ti ko si ni akẹgbẹ.
AR-ROBB: Ìtumọ̀ rẹ ni Oludẹdaa, Olukapa, Olupese, Oluṣeto ni Oun nikan ṣoṣo, mimọ fun Un.
AS-SAMIIHU: Ẹni tí igbọran Rẹ kari gbogbo nnkan, O si n gbọ gbogbo ohun tòun ti bi o ṣe pe oríṣiríṣi.
AL-BASIIR: Ẹni tí O ṣe pe O n ri gbogbo nnkan, O si n ri gbogbo nnkan boya o kere ni tabi o tobi.
AL-HALIIM: Oun ni imọ Rẹ kari gbogbo nnkan lori ohun ti o ti lọ tabi ti n ṣẹlẹ lọwọ tabi ti yoo pada ṣẹlẹ lọjọ iwaju.
AR-RAHMAAN: Ẹni tí O ṣe pe ikẹ Rẹ kari gbogbo ẹda Rẹ ati gbogbo nǹkan ti n ṣẹmi, gbogbo ẹrusin ati ẹda ni n bẹ labẹ ikẹ Rẹ.
AR-ROZZAAQ: Ọba ti ijẹẹmu gbogbo ẹda ninu eeyan, alijannu ati gbogbo ẹranko n bẹ ni ọwọ Rẹ.
AL-HAYY: Alaaye ti ko nii ku, gbogbo ẹda ni yoo si ku.
"Ọba Ńlá:
Ẹni ti O jẹ pe gbogbo pipe nbẹ fun Un ati gbogbo titobi nibi awọn orukọ Rẹ ati awọn iroyin Rẹ ati awọn iṣẹ Rẹ."

"Idahun- a maa nífẹ̀ẹ́ wọn, a maa ṣẹri pada si ọdọ wọn nipa awọn àlámọ̀rí ati awọn iṣẹlẹ ọtun ti sharia, ki a ma darukọ wọn afi pẹlu daada, ẹnikẹ́ni ti o ba darukọ wọn pẹlu nnkan miiran to yatọ si iyẹn ninu aburu; ko si ni oju-ọna. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
{Allāhu yóò ṣàgbéga àwọn ipò fún àwọn t’ó gbàgbọ́ ní òdodo àti àwọn tí A fún ní ìmọ̀ nínú yín. Allāhu sì ni Alámọ̀tán nípa ohun tí ẹ̀ ń ṣe níṣẹ́ 11} [Suuratul-Mujadila 11].

"Idahun- awọn ni onigbagbọ olubẹru. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Gbọ́, dájúdájú àwọn ọ̀rẹ́ Allāhu, kò níí sí ìbẹ̀rù (ìyà ọ̀run) fún wọn, wọn kò sì níí banújẹ́ (lórí oore ayé) 62 (Àwọn ni) àwọn t’ó gbàgbọ́ lódodo, wọ́n sì máa ń bẹ̀rù (Allāhu) 63} " [Suuratu Yunus: 62, 63].

"Idahun- igbagbọ maa n lekun pẹlu itẹle a si maa dínkù pẹlu ẹṣẹ. "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Àwọn onígbàgbọ́ òdodo ni àwọn t’ó jẹ́ pé nígbà tí wọ́n bá fi (ìyà) Allāhu ṣe ìrántí (fún wọn), ọkàn wọn yóò wárìrì, nígbà tí wọ́n bá sì ké àwọn āyah Rẹ̀ fún wọn, wọn yóò lékún ní ìgbàgbọ́ òdodo. Olúwa wọn sì ni wọ́n ń gbáralé 2} " "[Surah Al-Anfâl: 2]"

"Idahun- ki o maa jọsin fun Ọlọhun gẹgẹ bii pe o n ri I, ti o o ba ri I; dajudaju Oun n ri ẹ. "

"Idahun- pẹlu majẹmu meji: "
"1- ti o ba mọ́ kangá nitori ojú rere Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- "
"2- Ti o ba jẹ lori oju-ọna Anabi -ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a-. "

"Ibeere ogoji: Ki ni igbarale Ọlọhun -ti ọla Rẹ ga- "
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Àti pé ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé Allāhu, Ó máa tó o } "[Surah At-Talâq: 3]"
"{Hasbuhu} : tabi O maa to fun un. "

"Idahun- AL’MAHRUUF: Oun ni pipaṣe lati ṣe gbogbo itẹle Ọlọhun- Alagbara ti O gbọnngbọn-, AL-MUNKAR: Oun ni kikọ kuro nibi gbogbo ṣiṣẹ Ọlọhun Alagbara ti O gbọnngbọn.
Ọba ti ọla Rẹ ga sọ pe:
"{Ẹ jẹ́ ìjọ t’ó lóore jùlọ, tí A gbé dìde fún àwọn ènìyàn; ẹ̀ ń pàṣẹ ohun rere, ẹ̀ ń kọ ohun burúkú, ẹ sì gbàgbọ́ nínú Allāhu } "[Surah Âl-`Imrân: 110]"

"Idahun- awọn ni awọn to wa lori nnkan ti Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- wa lori ẹ ati awọn sàábé rẹ nibi ọrọ ati iṣẹ ati adisọkan. "
"Wọn sọ wọn ni oni sunnah:
Torí itẹle wọn ti wọn n tẹle oju-ọna Anabi- ki ikẹ Ọlọhun ati ọla Rẹ maa ba a- ati gbigbe adadaalẹ ju silẹ. "
"Wal Jamaa'ah:
Torí pe wọn kojọ lori ododo ti wọn ko si yapa nibẹ.